Láti ọ̀dọ̀ Umar ọmọ Al-Khattaab- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Oun gbọ ti Anọbi Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pe: “Ti o ba jẹ pe ẹ n...
Òjíṣẹ́ Ọlọhun, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, gba wa niyanju lati gbẹkẹle Ọlọhun lati mu anfaani wa ati lati yago fun ipalara ninu ọ̀rọ̀ aye ati ẹsin...
Lati ọdọ Abu Hurairah - ki Ọlọhun yọnu si i - ó ṣo pé: Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - sọ pe: «Ẹni ti o n gun nkan ni o maa salamọ s...
Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ṣe itọsọna lọ sibi ẹkọ sisalamọ laarin awọn eeyan "As salaamu alaykum wa rahmotuLloohi wabarakātuHu". Ọmọde o...
Láti ọ̀dọ̀ Abu Dharr- ki Ọlọhun yọnu si i-: Láti ọ̀dọ̀ Anọbi- ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a- ninu ohun ti o gba wa lati ọdọ Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- O s...
Ojiṣẹ Ọlọhun, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, ṣe alaye pe Ọlọhun Ọba sọ wipe Oun ti ṣe àbòsí ni eewọ fun ara Oun, O si ṣe àbòsí ni eewọ láàrin àwọn ẹ̀...
Lati ọdọ Jaabir ọmọ Abdullahi- ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji- dajudaju ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: "Ẹ paya abosi, nitor...
Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ṣekilọ kuro nibi abosi, ninu rẹ ni: Ṣíṣe abosi awọn eniyan ati abosi ara ẹni ati ṣíṣe abosi nibi iwọ Ọlọhun-...
Láti ọ̀dọ̀ Abu Musa- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Dájúdájú Ọlọhun maa n lọ́ alabosi lára, t...
Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n ṣọ wa lara kúrò nibi itẹsiwaju ninu abosi dídá ẹṣẹ ati ṣíṣe ẹbọ, ati ṣíṣe abosi fun awọn èèyàn nibi ẹ̀tọ́...

Láti ọ̀dọ̀ Umar ọmọ Al-Khattaab- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Oun gbọ ti Anọbi Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pe: “Ti o ba jẹ pe ẹ n gbẹkẹle Ọlọhun gẹgẹ bi o ti yẹ ki ẹ gbẹkẹle E ni, Oun iba pese fun yin gẹ́gẹ́ bí O ti pese fun awọn ẹyẹ, ti wọn maa jade ni owurọ pẹlu ebi, ti wọn si maa pada ni irọlẹ ti wọn si ti yó.”

Lati ọdọ Abu Hurairah - ki Ọlọhun yọnu si i - ó ṣo pé: Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - sọ pe: «Ẹni ti o n gun nkan ni o maa salamọ si ẹni ti o n rin, ẹni ti o n rin ni o máa salamọ si ẹni ti o jokoo, awọn ti onka wọn kere ni wọ́n maa salamọ si awọn ti onka wọn pọ».

Láti ọ̀dọ̀ Abu Dharr- ki Ọlọhun yọnu si i-: Láti ọ̀dọ̀ Anọbi- ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a- ninu ohun ti o gba wa lati ọdọ Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- O sọ pe: “Ẹ̀yin ẹrusin Mi, Emi ṣe abosi ni eewọ fun ara Mi, Mo si ṣe e ni eewọ laarin yin, ẹ ma ṣe abosi si ara yin, ẹ̀yin ẹrú Mi, gbogbo yin ni ẹ sọnù, ayafi ẹni tí Mo ba ṣe imọna fun; nitori naa ẹ wa imọna lọ́dọ̀ Mi, Emi yoo si ṣe amọna yin, ẹyin ẹrú Mi, ebi n pa gbogbo yin ayafi ẹni ti mo ba bọ́; nitori náà, ẹ wá oúnjẹ lọ́dọ̀ Mi, èmi yóò sì bọ́ yín. Ẹ̀yin ẹrú Mi, gbogbo yin ni ẹ wa ni ihoho ayafi eni ti Mo ba da aṣọ bo; nitori naa ẹ wa dida aṣọ bo yin lọ́dọ̀ Mi, maa da aṣọ bo yín, ẹ̀yin ẹrú Mi, ẹ n da ẹṣẹ loru ati ni ọsan, Mo si maa n ṣe aforijin àwọn ẹṣẹ pata, ki ẹ yaa wa aforijin Mi, maa forí jin yin, ẹyin ẹrú Mi, ẹ ko le de ibi ìnira Mi débi pé ẹ maa ni Mi lara, ẹ ko si lee debi anfaani Mi debi pe ẹ maa ṣe mi ni anfaani. Ẹyin ẹrusin Mi, ti ẹni akọkọ yin ati ẹni ti o kẹhin ninu yin, eniyan yin ati awọn alujannu yin, tí wọ́n ba wa lori ọkàn arákùnrin kan ti o páyà Ọlọhun jù lọ ninu yin, iyẹn ko le nǹkan kan kun ninu ọla Mi. Ẹyin ẹrusin Mi, ti ẹni akọkọ yin ati ẹni ti o kẹhin ninu yin, eniyan yin ati awọn alujannu yin, tí wọ́n ba wa lori ọkàn arákùnrin kan ti o yapa Ọlọhun jù lọ ninu yin, iyẹn ko din nǹkan kan kù ninu ọla Mi. Ẹyin ẹrusin Mi, ti ẹni akọkọ yin ati ẹni ti o kẹhin ninu yin, eniyan yin ati awọn alujannu yin, tí wọ́n ba dúró lórí ilẹ̀ kan, ki wọn wa maa tọrọ lọ́wọ́ Mi, ki n wa maa fun èèyàn kọ̀ọ̀kan ni ohun ti n beere, ìyẹn ko din nǹkan kan ku ninu ohun ti n bẹ lọdọ Mi, àyàfi gẹgẹ bii ohun ti abẹrẹ maa dinku ti wọn ba ki i bọ inu omi òkun, ẹyin ẹrusin Mi, Mo n ṣe akọsilẹ iṣẹ yin fun yin, lẹyin naa Mo maa san ẹsan rẹ fun yin, ẹnikẹni ti o ba ri oore, ki o dúpẹ́ fun Ọlọhun, ẹni ti o ba si ri yatọ si iyẹn, ki o ma ṣe bu ẹnikan ayafi ara rẹ”.

Lati ọdọ Jaabir ọmọ Abdullahi- ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji- dajudaju ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: "Ẹ paya abosi, nitori pe abosi jẹ awọn okunkun ni ọjọ igbedide, ẹ paya ahun, nitori pe ahun lo pa awọn ti wọn ṣáájú yin run, o ti wọn lati maa ta awọn ẹjẹ wọn silẹ wọn si sọ awọn eewọ wọn di ẹtọ"

Láti ọ̀dọ̀ Abu Musa- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Dájúdájú Ọlọhun maa n lọ́ alabosi lára, titi ti yoo fi mu u ti ko si nii jẹ ki ó bọ́”, o sọ pe: Lẹ́yìn náà ni o ka: “{Báyẹn ni ìgbámú Olúwa rẹ. Nígbà tí Ó bá gbá àwọn ìlú alábòsí mú, dájúdájú Ó máa gbá a mú pẹ̀lú ìyà ẹlẹ́ta-eléro t’ó le} [Huud: 102]”

Lati ọdọ Ibnu Abbaas (ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji) Lati ọdọ Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ninu nǹkan ti o gba wa lati ọdọ Oluwa rẹ ti O lágbára ti O gbọnngbọn, o sọ pé: “Dájúdájú Ọlọhun kọ daadaa ati aburu, lẹyin naa O ṣalaye ìyẹn, ẹni tí ó bá gbèrò dáadáa, ti ko wa ṣe e, Ọlọhun maa kọ ọ fun un ni ọdọ Rẹ ni dáadáa ti o pé, ti o ba wa gbero rẹ, ti o wa ṣe e, Ọlọhun maa kọ ọ fun un ni ọdọ Rẹ ni dáadáa mẹ́wàá titi de ìlọ́po ẹẹdẹgbẹrin, titi de ìlọ́po ti o pọ̀, ẹni ti o ba gbèrò aburu, ti ko wa ṣe e, Ọlọhun maa kọ ọ fun un ni ọdọ Rẹ ni dáadáa ti o pe, ti o ba wa gbero rẹ ti o si ṣe e, Ọlọhun maa kọ ọ fun un ni aburu ẹyọkan”.

Lati ọdọ Ibnu Mas’ud- ki Ọlọhun yọnu si i-, o sọ pe: Arakunrin kan sọ pe: Irẹ Òjíṣẹ́ Ọlọhun, njẹ wọn maa ba wa wí nípa nnkan ti a ṣe ni asiko aimọkan? O sọ pe: “Ẹni ti o ba ṣe daadaa ninu Isilaamu wọn ko nii ba a wí nípa nnkan ti o ṣe ni asiko aimọkan, ati pe ẹni ti o ba ṣe aburu ninu Isilaamu wọn maa ba a wí nípa akọkọ ati igbẹyin”.

Lati ọdọ ọmọ Abbās – ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji: Dajudaju awọn eeyan kan ninu awọn ẹlẹbọ (awọn ti wọn mu orogun mọ Ọlọhun), ti wọn si pa ọpọlọpọ eeyan, ti wọn tun ti ṣe ọpọlọpọ agbere, ni wọn wa ba Muhammad – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – ni wọn wa sọ fun un pe: Dajudaju nkan ti o n sọ ti o si n pepe si, nkan ti o daa ni, ti o ba fun wa niroo pe aforijin n bẹ fun nkan ti a ṣe, nigba naa ni o sọkalẹ pe {(Àwọn ni) àwọn tí kò pe ọlọ́hun mìíràn mọ́ Allāhu. Wọn kò pa ẹ̀mí tí Allāhu ṣe (pípa rẹ̀) ní èèwọ̀ àfi ní ọ̀nà ẹ̀tọ́. Àti pé wọn kò ṣe zinā}[Al-Furqān: 68], o tun sọkalẹ pe: {Sọ pé: “Ẹ̀yin ẹrúsìn Mi, tí ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ sí ẹ̀mí ara yín lọ́rùn, ẹ má ṣe sọ̀rètí nù nípa ìkẹ́ Allāhu}[Az-Zumar: 53].

Lati ọdọ Hakeem ọmọ Hizaam- ki Ọlọhun yọnu si i-, o sọ pe: Mo sọ pé: Irẹ Òjíṣẹ́ Ọlọhun, fun mi ni iro nipa nnkan ti mo maa n se wọn ni asiko aimọkan bii saara ṣíṣe ati bibọkun kúrò lọrun ẹru ati dida ibi pọ, njẹ ẹsan wa nibẹ? Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “O gba Isilaamu lori nnkan ti o ṣáájú ninu daadaa”.

Lati ọdọ Anas ọmọ Malik- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Dajudaju Ọlọhun ko nii ṣe abosi olugbagbọ kan ni ti daadaa ti o ba ṣe, wọn yoo fun un ni ẹsan rẹ ni aye, wọn si tun maa san an ni ẹsan pẹlu rẹ ni ọrun, sugbọn alaigbagbọ wọn maa fun un ni oúnjẹ jẹ pẹlu awọn daadaa nnkan ti o ba ṣe ni iṣẹ́ nitori Ọlọhun ni aye, ti o ba ti wa de ọrun, daadaa kan ko nii maa jẹ tirẹ ti wọn maa san an lẹsan pẹlu rẹ”.

Láti ọ̀dọ̀ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i-: Lati ọdọ Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-, ninu nǹkan ti o gba wa lati ọdọ Olúwa rẹ tí Ó lágbára ti O gbọnngbọn, O sọ pe: “Ẹru mi da ẹṣẹ kan, o wa sọ pé: Irẹ Ọlọhun, fi orí ẹṣẹ mi jin mi, Ọlọhun Àlekè-ọla wa sọ pé: Ẹrú Mi da ẹṣẹ kan, o si mọ pe oun ni Olúwa kan ti maa n ṣe àforíjìn ẹṣẹ, ti O si maa n fi iya ẹṣẹ jẹ eeyan, lẹyin naa o tun ṣẹri pada si idi ẹṣẹ, o wa tun sọ pé: Irẹ Oluwa mi, fi ori ẹṣẹ mi jin mi, Ọlọhun ti ọla Rẹ ga tun sọ pé: Ẹrú Mi da ẹṣẹ kan, o si mọ pe oun ni Olúwa kan ti maa n ṣe àforíjìn ẹṣẹ, ti O si maa n fi iya ẹṣẹ jẹ eeyan, lẹyin naa o tun ṣẹri pada si idi ẹṣẹ, o wa tun sọ pé: Irẹ Oluwa mi, fi ori ẹṣẹ mi jin mi, Ọlọhun ti ọla Rẹ ga tun sọ pé: Ẹrú Mi da ẹṣẹ kan, o si mọ pe oun ni Olúwa kan ti maa n ṣe àforíjìn ẹṣẹ, ti O si maa n fi iya ẹṣẹ jẹ eeyan, maa ṣe ohun ti o ba fẹ́, mo ti fi ori jin ọ”.

Lati ọdọ ‘Aliyy o sọ pe: Dajudaju mo jẹ ọkunrin kan ti o ṣe pe ti mo ba ti gbọ ọrọ kan lati ọdọ ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - Ọlọhun maa n fi nkan ti O ba fẹ ṣe mi ni anfaani pẹlu rẹ, ti ẹnikẹni ba wa sọrọ fun mi ninu awọn saabe rẹ (Anabi) maa ni ki o bura, ti o ba ti wa bura fun mi maa gba a gbọ, Abubakar wa sọrọ fun mi, ododo si ni Abubakar sọ, o sọ pe: Mo gbọ ti ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - n sọ pe: «Ko si ẹnìkankan ti yio da ẹṣẹ kan, lẹyin naa ni o wa dide ti o si ṣe imọra, lẹyin naa ni o wa kirun, lẹyin naa o wa aforijin Ọlọhun, ayaafi ki Ọlọhun ṣe aforijin fun un», lẹyin naa ni o wa ka aaya yii: {Àwọn tí (ó jẹ́ pé) nígbà tí wọ́n bá ṣe ìbàjẹ́ kan tàbí tí wọ́n bá ṣàbòsí sí ẹ̀mí ara wọn, wọ́n á rántí Allāhu, wọ́n á sì tọrọ àforíjìn fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn} [Āl ‘Imraan: 135].