/ “Ọlọhun sọ pe: Maa na owó irẹ ọmọ Anọbi Adam, Ọlọhun maa fi òmíràn rọ́pò”

“Ọlọhun sọ pe: Maa na owó irẹ ọmọ Anọbi Adam, Ọlọhun maa fi òmíràn rọ́pò”

Lati ọdọ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- pe ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pé: “Ọlọhun sọ pe: Maa na owó irẹ ọmọ Anọbi Adam, Ọlọhun maa fi òmíràn rọ́pò”.
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pe Ọlọhun sọ pe: Irẹ ọmọ Adam, maa ná owó- ninu awọn ìnáwó ti o jẹ dandan ati eyi ti a fẹ́- maa gbòòrò arisiki rẹ, maa si fi òmíràn rọ́pò, maa si ba ọ fi alubarika si i.

Hadeeth benefits

  1. Ṣiṣenilojukokoro lori saara ṣíṣe ati ninawo si oju ọna Ọlọhun.
  2. Ninawo sibi nnkan ti o loore wa ninu awọn okùnfà ìbùkún ti o tobi ju ninu arisiki ati ṣíṣe adipele rẹ, ati ki Ọlọhun fi òmíràn rọ́pò fun ẹrú.
  3. Hadiisi yii wa nínú ohun ti Anabi, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun o maa ba a, gba wa lati ọdọ Oluwa rẹ, ati pe a n pe e ni Hadith Qudsiy tabi Hadith Ilaahiy, oun ni eyi ti gbólóhùn rẹ ati itumọ rẹ wa lati ọdọ Ọlọhun, sibẹsibẹ, ko ni awọn ìròyìn Al-Qur’an ti o ṣe iyatọ rẹ si ohunkohun miiran, gẹgẹ bii ìjọsìn pẹ̀lú kika rẹ, ati ṣíṣe imọra ti a ba fẹ kà á, ati ipenija, ati àìní ikapa lati mu irú rẹ wa, ati bẹẹ bẹẹ lọ.